1 Ní ọjọ́ náà,OLUWA yóo fi idà rẹ̀ tí ó mú, tí ó tóbi, tí ó sì lágbára,pa Lefiatani, ejò tí ó ń fò,Lefiatani, ejò tí ń lọ́ wérékéké,yóo sì pa ejò ńlá tí ń bẹ ninu òkun.
2 Ní ọjọ́ náà,OLUWA yóo kọrin nípa ọgbà àjàrà dáradára kan pé,
3 “Èmi OLUWA ni olùṣọ́ rẹ̀,lásìkò, lásìkò ni mò ń bomi rin ín;tọ̀sán-tòru ni mò ń ṣọ́ ọkí ẹnìkan má baà bà á jẹ́.
4 Inú kò bí mi,ǹ bá rí ẹ̀gún ati pàǹtí ninu rẹ̀,ǹ bá gbógun tì wọ́n,ǹ bá jó gbogbo wọn níná papọ̀.
5 Ṣugbọn bí wọn bá fi mí ṣe ààbò,kí wọn wá kí á parí ìjà láàrin ara wa;kí wọn wá kí á parí ìjà láàrin ara wa.”
6 Ní ọjọ́ iwájúJakọbu yóo ta gbòǹgbò,Israẹli yóo tanná, yóo rúwé,yóo so, èso rẹ̀ yóo sì kún gbogbo ayé.
7 Ṣé OLUWA ti jẹ wọ́n níyà bí ó ti fìyà jẹ àwọn tí ó jẹ wọ́n níyà?Ṣé ó ti pa wọ́n bí ó ti pa àwọn tí ó pa wọ́n?