Aisaya 30:14-20 BM

14 Wíwó rẹ̀ yóo dàbí ìgbà tí eniyan la ìkòkò mọ́lẹ̀,tí ó fọ́ yángá-yángá,tóbẹ́ẹ̀ tí eniyan kò rí àpáàdì kan mú jáde ninu rẹ̀,tí a lè fi fọn iná ninu ààrò,tabi èkúfọ́, tí a lè fi bu omi ninu odò.”

15 Nítorí OLUWA Ọlọrun, Ẹni Mímọ́ Israẹli ní:“Bí ẹ bá yipada, tí ẹ sì farabalẹ̀,ẹ óo rí ìgbàlà;bí ẹ bá dákẹ́ jẹ́ẹ́ tí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọrun,ẹ óo lágbára.Ṣugbọn ẹ kọ̀.

16 Ẹ sọ pé ó tì o, ẹ̀yin óo gun ẹṣin sálọ ni.Nítorí náà sísá ni ẹ óo sálọ.Ẹ sọ pé ẹṣin tí ó lè sáré ni ẹ óo gùn.Nítorí náà àwọn tí yóo máa le yín,wọn óo lè sáré gan-an ni.

17 Ẹgbẹrun ninu yín yóo sá fún ẹyọ ọ̀tá yín kan,gbogbo yín yóo sì sá fún ẹyọ eniyan marun-untítí tí àwọn tí yóo kú ninu yín yóo fi dàbí igi àsíá lórí òkè.Wọn óo dàbí àsíá ati àmì lórí òkè.”

18 Nítorí náà OLUWA ń dúró dè yín,ó ti ṣetán láti ṣàánú yín.Yóo dìde, yóo sì ràn yín lọ́wọ́.Nítorí Ọlọrun Olódodo ni OLUWA.

19 Ẹ̀yin ará Sioni tí ẹ̀ ń gbé Jerusalẹmu, ẹ kò ní sọkún mọ́. OLUWA yóo ṣàánú yín nígbà tí ẹ bá ké pè é, yóo sì da yín lóhùn nígbà tí ó bá gbọ́ igbe yín.

20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé OLUWA yóo jẹ́ kí ẹ ní ọpọlọpọ ìṣòro, yóo sì jẹ́ kí ẹ ṣe ọpọlọpọ wahala, sibẹsibẹ olùkọ́ yín kò ní farapamọ́ fun yín mọ́, ṣugbọn ẹ óo máa fi ojú yín rí i.