Aisaya 31:1-7 BM

1 Àwọn tí ó ń lọ sí Ijipti fún ìrànlọ́wọ́ gbé!Àwọn tí wọ́n gbójú lé ẹṣin;tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé kẹ̀kẹ́ ogun nítorí pé wọ́n pọ̀,tí wọ́n gbójú lé ẹṣinnítorí pé wọ́n lágbára!Wọn kò gbójú lé Ẹni Mímọ́ Israẹli,wọn kò sì wádìí ọ̀rọ̀ lọ́dọ̀ OLUWA.

2 Bẹ́ẹ̀ ni ó gbọ́n,ó sì mọ ọ̀nà tí ó fi lè mú kí àjálù dé bá eniyan,kì í sọ̀rọ̀ tán, kó yí ọ̀rọ̀ rẹ̀ pada.Ṣugbọn yóo dìde sí ìdílé àwọn aṣebi,ati àwọn tí ń ti àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ lẹ́yìn.

3 Eniyan sá ni àwọn ará Ijipti,wọn kìí ṣe Ọlọrun.Ẹranko lásán sì ni ẹṣin wọnwọn kì í ṣe àǹjọ̀nnú.Bí OLUWA bá na ọwọ́, tí ó bá gbá wọn mú,ẹni tí ń ranni lọ́wọ́ yóo fẹsẹ̀ kọ,ẹni tí à ń ràn lọ́wọ́ yóo ṣubú;gbogbo wọn yóo sì jọ ṣègbé pọ̀.

4 Nítorí OLUWA sọ fún mi pé,“Bí kinniun tabi ọmọ kinniunti máa ń kùn lórí ẹran tí ó bá pa,tí kìí bìkítà fún igbe àwọn olùṣọ́ aguntan,tí wọ́n pera wọn jọ, tí wọn ń bọ̀,tí ẹ̀rù ariwo wọn kìí sìí bà á;bẹ́ẹ̀ ni OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo sọ̀kalẹ̀,yóo wá jà lórí òkè Sioni ati àwọn òkè tí ó yí Sioni ká.

5 Bí àwọn ẹyẹ tií da ìyẹ́ bo ìtẹ́ wọn,bẹ́ẹ̀ ni OLUWA àwọn ọmọ ogunyóo dáàbò bo Jerusalẹmu,yóo dáàbò bò ó, yóo sì gbà á sílẹ̀yóo dá a sí, yóo sì yọ ọ́ kúrò ninu ewu.”

6 Ẹ̀yin ọmọ Israẹli,ẹ pada sọ́dọ̀ ẹni tí ẹ ti ṣàìgbọràn sí lọpọlọpọ.

7 Nítorí pé ní ọjọ́ náà, olukuluku yóo gbé àwọn ère fadakaati ère wúrà tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ ṣe sọnù,àwọn ère tí ó mú wọn dẹ́ṣẹ̀.