17 Ojú yín yóo rí ọba ninu ọlá ńlá rẹ̀;ẹ óo fojú yín rí ilẹ̀ tí ó lọ salalu.
18 Ẹ óo máa ronú ìnira tí ẹ ti ní pé:“Níbo ni akọ̀wé wà?Níbo ni ẹni tí ń gba owó orí wà?Níbo sì ni ẹni tí ń ka ilé ìṣọ́ wà?”
19 Ẹ kò ní rí àwọn aláfojúdi náà mọ́,àwọn tí wọn ń fọ èdè tí kò ní ìtumọ̀ si yín,tí wọn ń kólòlò ní èdè tí ẹ kò gbọ́.
20 Ẹ wo Sioni, ìlú tí a yà sọ́tọ̀ fún àjọ̀dún.Ẹ óo fi ojú rí Jerusalẹmu, ibùgbé alaafia, tí àgọ́ rẹ̀ kò ní ṣídìí,tí èèkàn tí a fi kàn án mọ́lẹ̀ kò ní hú laelae,bẹ́ẹ̀ ni okùn tí a fi so ó mọ́lẹ̀ kò ní já.
21 Ṣugbọn níbẹ̀ ni OLUWA, ninu ògo rẹ̀,yóo jẹ́ odò ńlá ati odò tí ń ṣàn fún wa;níbi tí ọkọ̀ ọlọ́pọ́n kò lè dé,ọkọ̀ ojú omi kò sì ní lè kọjá níbẹ̀.
22 Nítorí pé OLUWA ni onídàájọ́ wa,òun ni alákòóso wa;OLUWA ni ọba wa,òun ni yóo gbà wá là.
23 Okùn òpó-ọkọ̀ rẹ̀ ti tú,kò lè mú òpó-ọkọ̀ náà dáradára ní ipò rẹ̀ mọ́;kò sì lè gbé ìgbòkun dúró.A óo pín ọpọlọpọ ìkógun nígbà náà,kódà, àwọn arọ pàápàá yóo pín ninu rẹ̀.