Aisaya 44:19-25 BM

19 Kò sí ẹni tí ó ronú wò, tabi tí ó ní ìmọ̀ tabi òye, láti wí pé: “Ìdajì igi yìí ni mo fi dáná tí mo fi se oúnjẹ, tí mo sì fi se ẹran tí mo jẹ. Kí ló wá dé tí n óo ṣe fi ìyókù gbẹ́ ère kí n máa bọ ọ́? Ṣé ìtì igi lásán ló yẹ kí n máa foríbalẹ̀ fún, kí n máa bọ?”

20 Kò yàtọ̀ sí ẹni tí ń pe eérú ní oúnjẹ. Èrò ẹ̀tàn ti ṣì í lọ́nà, kò sì lè gba ara rẹ̀ kalẹ̀ tabi kí ó bi ara rẹ̀ pé, “Ǹjẹ́ irọ́ kọ́ ni ohun tí ó wà lọ́wọ́ mi yìí?”

21 Jakọbu, ranti àwọn nǹkan wọnyi,nítorí pé iranṣẹ mi ni ọ́, ìwọ Israẹli.Èmi ni mo ṣẹ̀dá rẹ, iranṣẹ mi ni ọ́,n kò jẹ́ gbàgbé rẹ, Israẹli.

22 Mo ti ká àìdára rẹ kúrò bí awọsanma,mo ti gbá ẹ̀ṣẹ̀ rẹ dànù bí ìkùukùu.Pada sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ pada.

23 Ẹ hó ìhó ayọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí OLUWA ti ṣe é.Ẹ pariwo, ẹ̀yin ìsàlẹ̀ ilẹ̀.Ẹ kọrin, ẹ̀yin òkè ńlá, ìwọ igbó ati igi inú rẹ̀,nítorí OLUWA ti ra Jakọbu pada,yóo sì ṣe ara rẹ̀ lógo ní Israẹli.

24 Gbọ́ ohun tí OLUWA, Olùràpadà rẹ wí,ẹni tí ó ṣẹ̀dá rẹ láti inú oyún.Ó ní, “Èmi ni OLUWA, tí mo dá ohun gbogbo.Èmi nìkan ni mo tẹ́ ojú ọ̀run,tí mo sì dá ilẹ̀ ayé tẹ́,

25 èmi tí mo sọ àmì àwọn tí ń woṣẹ́ èké di asán,tí mo sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀.Mo yí ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n pomo sì sọ ọgbọ́n wọn di òmùgọ̀.