Aisaya 45:17-23 BM

17 Ṣugbọn OLUWA gba Israẹli là,títí ayé sì ni ìgbàlà rẹ̀.Ojú kò ní tì ọ́, bẹ́ẹ̀ ni o kò ní dààmú, títí lae.

18 Ẹ gbọ́ ohun tí OLUWA wí,OLUWA tí ó dá ọ̀run. (Òun ni Ọlọrun.)Òun ni ó dá ilẹ̀, tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀,kò dá a ninu rúdurùdu,ṣugbọn ó dá a kí eniyan lè máa gbé inú rẹ̀Ó ní, “Èmi ni OLUWA, kò sí Ọlọrun mìíràn.

19 N kò sọ ọ́ níkọ̀kọ̀, ninu òkùnkùn.N kò sọ fún arọmọdọmọ Jakọbu pé:‘Ẹ máa wá mi ninu rúdurùdu.’Òtítọ́ ni Èmi OLUWA sọ.Ohun tí ó tọ́ ni mò ń kéde.”

20 OLUWA ní:“Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ wá,ẹ jọ súnmọ́ bí,gbogbo ẹ̀yin tí ẹ kù ninu àwọn orílẹ̀-èdè.Aláìlóye ni àwọn tí ń gbẹ́ ère igi lásán kiri,tí wọ́n sì ń gbadurasí oriṣa tí kò lè gbànìyàn là.

21 Ẹ sọ̀rọ̀ jáde, kí ẹ sì ro ẹjọ́ tiyín,jẹ́ kí wọ́n jọ gbìmọ̀ pọ̀.Ta ló sọ èyí láti ìgbà laelae?Ta ló kéde rẹ̀ láti ìgbà àtijọ́?Ṣebí èmi OLUWA ni?Kò tún sí Ọlọrun mìíràn lẹ́yìn mi.Ọlọrun Olódodo ati Olùgbàlàkò tún sí ẹnìkan mọ́, àfi èmi.

22 “Ẹ yipada sí mi kí á gbà yín là,gbogbo ẹ̀yin òpin ayé.Nítorí èmi ni Ọlọrun,kò tún sí ẹlòmíràn mọ́.

23 Mo ti fi ara mi búra,mo sì fi ẹnu mi sọ̀rọ̀ pẹlu òtítọ́ inú,ọ̀rọ̀ tí kò ní yipada:‘Gbogbo orúnkún ni yóo wólẹ̀ fún mi,èmi ni gbogbo eniyan yóo sì búra pé àwọn óo máa sìn.’