6 N óo jẹ́ kí ó di igbó,ẹnikẹ́ni kò ní ro ó mọ́,wọn kò sì ní tọ́jú rẹ̀ mọ́.Ẹ̀gún ati ẹ̀wọ̀n agogo ni yóo hù níbẹ̀.N óo pàṣẹ fún òjòkí ó má rọ̀ sórí rẹ̀ mọ́.
7 Nítorí ilé Israẹli ni ọgbà àjàrà OLUWA ọmọ ogun,àwọn ará Juda ni àjàrà dáradára tí ó gbìn sinu rẹ̀.Ó ń retí kí wọn máa ṣe ẹ̀tọ́,ṣugbọn kàkà bẹ́ẹ̀ wọ́n ń paniyan;ó ń retí ìwà òdodo,ṣugbọn kàkà bẹ́ẹ̀, àwọn tí wọn ń ni lára ni wọ́n ń kígbe.
8 Ègbé ni fún àwọn tí ó ń kọ́lé mọ́lé,tí wọn ń gba ilẹ̀ kún ilẹ̀,títí tí kò fi sí ilẹ̀ mọ́,kí ẹ̀yin nìkan baà lè máa gbé ilẹ̀ náà.
9 OLUWA ọmọ ogun ti búra lójú mi, ó ní,“Láìsí àní-àní, ọpọlọpọ ilé ni yóo di ahoro,ọ̀pọ̀ ilé ńláńlá, ati ilé dáradára yóo sì wà láìsí olùgbé.
10 Apẹ̀rẹ̀ èso àjàrà kan ni a óo rí ká ninu ọgbà àjàrà sarè mẹ́wàá.Kóńgò èso kan ni ẹni tí ó gbin kóńgò marun-un yóo rí ká.”
11 Ègbé ni fún àwọn tí wọ́n jí ní òwúrọ̀ kutukutu,láti máa wá ọtí líle kiri,tí wọ́n ń mu ún títí di ìrọ̀lẹ́,títí tí ọtí yóo fi máa pa wọ́n!
12 Dùùrù, hapu, ìlù, fèrè ati ọtí waini wà níbi àsè wọn;ṣugbọn wọn kì í bìkítà fún iṣẹ́ Ọlọrun,wọn kìí sìí náání iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.