Aisaya 58:6-12 BM

6 “Ṣebí irú ààwẹ̀ tí mo yàn ni pé:kí á tú ìdè ìwà burúkú,kí á yọ irin tí a fi di igi àjàgà;kí á dá àwọn tí ìyà ń jẹ sílẹ̀ lọ́fẹ̀ẹ́,kí á já gbogbo àjàgà?

7 Àní kí ẹ fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ,kí ẹ mú àwọn òtòṣì aláìnílé wá sinu ilé yín,bí ẹ bá rí ẹnikẹ́ni ní ìhòòhò, kí ẹ fi aṣọ bò ó,kí ẹ má sì fojú pamọ́ fún ẹni tí ó jẹ́ ẹbí yín.

8 “Nígbà náà ni ìmọ́lẹ̀ yín yóo tàn bí ìgbà tí ilẹ̀ ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ́,ara yín yóo sì tètè yá.Òdodo yín yóo máa tàn níwájú yín.Ògo mi yóo ṣe ààbò lẹ́yìn yín.

9 Ẹ óo ké pè mí nígbà náà,n óo sì da yín lóhùn.Ẹ óo kígbe pè mí,n óo sì dáhùn pé, ‘Èmi nìyí.’“Bí ẹ bá mú àjàgà kúrò láàrin yín,tí ẹ kò fi ìka gún ara yín nímú mọ́,tí ẹ kò sì sọ ọ̀rọ̀ ibi mọ́.

10 Bí ẹ bá ṣe làálàá láti fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ,tí ẹ sì wá ọ̀nà ìtẹ́lọ́rùn fún ẹni tí ìyà ń jẹ,ìmọ́lẹ̀ yín yóo tàn ninu òkùnkùn,òkùnkùn biribiri yín yóo dàbí ọ̀sán.

11 N óo máa tọ yín sọ́nà nígbà gbogbo,n óo fi nǹkan rere tẹ yín lọ́rùn;n óo mú kí egungun yín ó le,ẹ óo sì dàbí ọgbà tí à ń bomi rin,ati bí orísun omi, tí omi rẹ̀ kì í gbẹ.

12 Ẹ óo tún odi yín tí ó ti wó lulẹ̀ mọ,ẹ óo sì gbé àwọn ìpilẹ̀ṣẹ̀ àtijọ́ dìde.Àwọn eniyan yóo máa pè yín ní alátùn-únṣe ibi tí odi ti wó,alátùn-únṣe òpópónà àdúgbò fún gbígbé.