4 Àwọn tí wọn ń jókòó sí itẹ́ òkú,tí wọn ń dúró níbi ìkọ̀kọ̀ lóru;àwọn tí wọn ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀,tí ìṣaasùn ọbẹ̀ wọn sì kún fún ẹran aláìmọ́.
5 Wọn á máa ké pé, “Yàgò lọ́nà. Má fara kàn mí,nítorí mo jẹ́ ẹni mímọ́ jù ọ́ lọ.”Ṣugbọn bí èéfín ni irú wọn rí ní ihò imú mi,bí iná tí ó ń jó lojoojumọ.
6 Wò ó! A ti kọ ọ́ sílẹ̀ níwájú mi pé,“N kò ní dákẹ́, ṣugbọn n óo gbẹ̀san.
7 N óo gbẹ̀san gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wọn lára wọn,ati ti àwọn baba wọn.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.Nítorí pé wọ́n ń sun turari lórí àwọn òkè ńlá,wọ́n sì ń fi mí ṣẹ̀sín lórí àwọn òkè kéékèèké.N óo san ẹ̀san iṣẹ́ wọn àtẹ̀yìnwá fún wọn.
8 “Bí eniyan tíí wòye pé ọtí wà lára ìdì èso àjàrà,tí wọn sìí sọ pé, ‘Ẹ má bà á jẹ́,nítorí ohun rere wà ninu rẹ̀,’bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣe nítorí iranṣẹ mi,n kò ní pa gbogbo wọn run.
9 N óo mú kí arọmọdọmọ jáde lára Jakọbu,àwọn tí yóo jogún òkè ńlá mi yóo sì jáde láti ara Juda.Àwọn tí mo ti yàn ni yóo jogún rẹ̀,àwọn iranṣẹ mi ni yóo sì máa gbé ibẹ̀.
10 Ilé Ṣaroni yóo di ibùjẹ ẹran,àfonífojì Akori yóo sì di ibi tí àwọn ẹran ọ̀sìn yóo máa dùbúlẹ̀ sí,fún àwọn eniyan mi, tí wọ́n wá mi.