Aisaya 66:3-9 BM

3 “Ati ẹni tí ó pa mààlúù rúbọ,ati ẹni tí ó pa eniyan;kò sí ìyàtọ̀.Ẹni tí ó fi ọ̀dọ́ aguntan rúbọ,kò yàtọ̀ sí ẹni tí ó lọ́ ajá lọ́rùn pa.Ati ẹni tí ó fi ọkà rúbọ,ati ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ rúbọ,bákan náà ni wọ́n rí.Ẹni tí ó fi turari ṣe ẹbọ ìrántí,kò sì yàtọ̀ sí ẹni tí ó súre níwájú oriṣa.Wọ́n ti yan ọ̀nà tí ó wù wọ́n,wọ́n sì ń fi tọkàntọkàn sin ohun ìríra wọn.

4 Èmi náà óo sì yan ìjìyà fún wọn,n óo jẹ́ kí ẹ̀rù wọn pada sórí wọn.Nítorí pé nígbà tí mo pè wọ́n, ẹnikẹ́ni wọn kò dáhùn;nígbà tí mo sọ̀rọ̀ fún wọn, wọn kò gbọ́,wọ́n ṣe ohun tí ó burú lójú mi,wọ́n yan ohun tí inú mi kò dùn sí.”

5 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ OLUWA,ẹ̀yin tí ẹ̀ ń wárìrì nítorí ọ̀rọ̀ rẹ̀:“Àwọn arakunrin yín tí wọn kórìíra yín,wọ́n tì yín síta nítorí orúkọ mi;wọ́n ní, ‘Jẹ́ kí OLUWA fi ògo rẹ̀ hàn,kí á lè rí ayọ̀ yín.’Ṣugbọn àwọn ni ojú yóo tì.

6 Ẹ gbọ́ ariwo ninu ìlú,ẹ gbọ́ ohùn kan láti inú Tẹmpili,ohùn OLUWA ni,ó ń san ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.

7 “Kí ó tó bẹ̀rẹ̀ sí rọbí, ó ti bímọ.Kí ìrora obí tó mú un,ó ti bí ọmọkunrin kan.

8 Ta ló gbọ́ irú èyí rí?Ta ló rí irú rẹ̀ rí?Ǹjẹ́ a lè bí ilẹ̀ ní ọjọ́ kan,tabi kí á bí orílẹ̀-èdè kan ní ọjọ́ kan?Ní kété tí Sioni bẹ̀rẹ̀ sí rọbí,ni ó bí àwọn ọmọ rẹ̀ ọkunrin.

9 Ṣé mo lè jẹ́ kí eniyan máa rọbí,kí n má jẹ́ kí ó bímọ bí?Èmi OLUWA, tí mò ń mú kí eniyan máa bímọ,ṣé, mo jẹ́ sé eniyan ninu?”