6 Àwọn kan ń kó ọpọlọpọ wúrà jáde ninu àpò,wọ́n sì ń wọn fadaka lórí ìwọ̀n.Wọ́n sanwó ọ̀yà fún alágbẹ̀dẹ wúrà, ó bá wọn fi dá oriṣa.Wọ́n wá ń foríbalẹ̀ fún un, wọ́n ń sìn ín.
7 Wọn á gbé e lé èjìká wọn,wọn á gbé e sípò rẹ̀, á sì dúró kabẹ̀.Kò ní le kúrò níbẹ̀ lọ sí ibìkankan.Bí eniyan bá ké pè é, kò lè gbọ́,kò lè yọ eniyan ninu ìṣòro rẹ̀.
8 “Ẹ ranti èyí, kí ẹ dà á rò,ẹ fi ọkàn rò ó, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀.
9 Ẹ ranti àwọn nǹkan ti àtijọ́,nítorí pé èmi ni Ọlọrun, kò sí Ọlọrun mìíràn mọ́.Èmi ni Ọlọrun, kò sí ẹni tí ó dà bí mi.
10 Láti ìbẹ̀rẹ̀ ni èmi tíí sọ ohun tí ó gbẹ̀yìn.Láti ìgbà àtijọ́,ni mo tí ń sọ àwọn nǹkan tí kò ì tíì ṣẹlẹ̀.Èmi a máa sọ pé: ‘Àbá mi yóo ṣẹ,n óo sì mú ìpinnu mi ṣẹ.’
11 Mo pe idì láti ìlà oòrùn,mo sì ti pe ẹni tí yóo mú àbá mi ṣẹ láti ilẹ̀ òkèèrè wá.Mo ti sọ̀rọ̀, n óo sì mú un ṣẹ,mo ti ṣe ìpinnu, n óo sì ṣe é.
12 “Ẹ fetí sí mi, ẹ̀yin aláìgbọràn, ẹ̀yin tí ẹ jìnnà sí ìgbàlà.