4 “Ẹ fetí sí mi, ẹ̀yin eniyan mi,ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè,òfin kan yóo ti ọ̀dọ̀ mi jáde,ìdájọ́ òdodo mi yóo jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún àwọn eniyan.
5 Ìdáǹdè mi súnmọ́ tòsí,ìgbàlà mi sì ti ń yọ bọ̀.Èmi ni n óo máa ṣe àkóso àwọn eniyan,àwọn erékùṣù yóo gbẹ́kẹ̀lé mi,ìrànlọ́wọ́ mi ni wọn yóo sì máa retí.
6 Ẹ gbójú sókè, ẹ wo ojú ọ̀run,kí ẹ sì wo ayé ní ìsàlẹ̀.Ọ̀run yóo parẹ́ bí èéfín,ayé yóo gbó bí aṣọ,àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ yóo sì kú bíi kòkòrò;ṣugbọn títí lae ni ìgbàlà mi,ìdáǹdè mi kò sì ní lópin.
7 “Ẹ̀yin tí ẹ mọ òdodo, ẹ gbọ́ ohùn mi,ẹ̀yin tí ẹ fi tọkàntọkàn gba òfin mi,ẹ má bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn eniyan;ẹ má sì jẹ́ kí yẹ̀yẹ́ wọn já a yín láyà.
8 Ikán yóo jẹ wọ́n bí aṣọ,kòkòrò yóo jẹ wọ́n bí òwú;ṣugbọn ìdáǹdè mi yóo wà títí lae,ìgbàlà mi yóo sì wà láti ìran dé ìran.”
9 Jí, jí! Dìde, OLUWA, jí pẹlu agbára;jí bí ìgbà àtijọ́,bí o ti ṣe sí ìran wa látijọ́.Ṣebí ìwọ ni o gé Rahabu wẹ́lẹwẹ̀lẹ,tí o fi idà gún diragoni?
10 Àbí ìwọ kọ́ ni o mú kí omi òkun gbẹ,omi inú ọ̀gbun ńlá;tí o sọ ilẹ̀ òkun di ọ̀nà,kí àwọn tí o rà pada lè kọjá?