20 Ṣùgbọ́n ní ti Ísímáélì, mo gbọ́ ohun tí ìwọ wí, èmi yóò bùkún fún-un ní tòótọ́, èmi ó sì mú un bí sí i, yóò sì pọ̀ sí i, òun yóò sì jẹ́ baba fún àwọn ọmọ-ọba méjìlá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀ èdè ńlá.
21 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú Ísáákì, ẹni tí Ṣárà yóò bí fún ọ ni ìwòyí àmọ́dún.”
22 Nígbà tí ó ti bá Ábúráhámù sọ̀rọ̀ tán, Ọlọ́run sì gòkè lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
23 Ní ọjọ́ náà gan-an ni Ábúráhámù mú Ísímáélì ọmọ rẹ̀ àti àwọn ẹrú tí a bí ní ilé rẹ̀ àti àwọn tí ó fi owó rà, ó sì kọ wọ́n ní ilà. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kọ gbogbo ọkùnrin tí ń bẹ ní ilé rẹ̀ ní ilà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa.
24 Ábúráhámù jẹ́ ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùnún (99) ọdún nígbà tí a kọ ọ́ ní ilà.
25 Ísímáélì ọmọ rẹ̀ jẹ́ ẹni ọdún mẹ́talá, (13).
26 Ábúráhámù pẹ̀lú rẹ̀ kọ ilà ní ọjọ́ náà gan-an.