Jẹ́nẹ́sísì 13 BMY

Ìpínyà Ábúrámù àti Lọ́tì

1 Ábúrámù sì gòkè láti Éjíbítì lọ sí Nẹ́gẹ́fù ní ìhà gúsù, pẹ̀lú aya rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní àti Lọ́tì pẹ̀lú.

2 Ábúrámù sì ti di ọlọ́rọ̀ gidigidi, ní ẹran-ọ̀sìn, ó ní fàdákà àti wúrà.

3 Láti Gúúsù, ó ń lọ láti ibìkan sí ibòmíràn títí ó fi dé ilẹ̀ Bẹ́tẹ́lì, ní ibi tí àgọ́ rẹ̀ ti wà ní ìṣáájú ri lágbedeméjì Bẹ́tẹ́lì àti Áì.

4 Ní ibi tí ó ti tẹ́ pẹpẹ sí rí tẹ́lẹ̀; Ábúrámù sì ké pe orúkọ Olúwa.

5 Lọ́tì, tí ó ń bá Ábúrámù kiri pẹ̀lú ní agbo ẹran, ọ̀wọ́ ẹran àti àwọn àgọ́ tirẹ̀.

6 Ṣùgbọ́n ilẹ̀ náà kò le gbà wọ́n tí wọ́n bá ń gbé pọ̀, nítorí, ohun-ìní wọn pọ̀ tóbẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, débi wí pé wọn kò le è gbé pọ̀.

7 Èdè àìyedè sì bẹ̀rẹ̀ láàrin àwọn darandaran Ábúrámù àti ti Lọ́tì. Àwọn ará a Kénánì àti àwọn ará Pérísítì sì ń gbé ní ilẹ̀ náà nígbà náà.

8 Ábúrámù sì wí fún Lọ́tì pé, “Mo fẹ́ kí a fòpin sí èdè àìyedè tí ó wà láàrin èmi àti ìwọ àti láàrin àwọn darandaran wa, nítorí pé ẹbí ni wá.

9 Gbogbo ilẹ̀ ha kọ́ nìyí níwájú rẹ? Jẹ́ kí a pínyà. Bí ìwọ bá lọ sí apá ọ̀tún, èmi yóò lọ sí apá òsì, bí ó sì ṣe òsì ni ìwo lọ, èmi yóò lọ sí apá ọ̀tún.”

10 Lọ́tì sì gbójú sókè, ó sì ri wí pé gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jọ́dánì ni omi rin dáradára bí ọgbà Olúwa, bí ilẹ̀ Éjíbítì, ní ọ̀nà Ṣóárì. (Èyí ní ìṣáájú kí Olúwa tó pa Ṣódómù àti Gòmórà run).

11 Nítorí náà Lọ́tì yan gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jọ́dánì yìí fún ara rẹ̀, ó sì ń lọ sí ọ̀nà ìlà oòrùn. Òun àti Ábúrámù sì pínyà.

12 Ábúrámù ń gbé ni ilẹ̀ Kénánì, Lọ́tì sì jókòó ní ìlú agbègbè àfonífojì náà, ó sì pàgọ́ rẹ̀ títí dé Ṣódómù.

13 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Ṣódómù jẹ́ ènìyàn búburú, wọn sì ń dẹ́sẹ̀ gidigidi ni ìwájú Olúwa.

14 Olúwa sì wí fún Ábúrámù lẹ́yìn ìpínyà òun àti Lọ́tí pé, “Gbé ojú rẹ sókè níṣinṣin yìí, kí o sì wò láti ibi tí o gbé wà a nì lọ sí ìhà àríwá àti sí ìhà gúsù, sí ìlà oòrùn àti sí ìwọ̀ rẹ̀.

15 Gbogbo ilẹ̀ tí ìwọ ń wò o nì ní èmi ó fi fún ọ àti irú ọmọ rẹ láéláé.

16 Èmi yóò mú kí irú ọmọ rẹ kí ó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀. Àyàfi bí ẹnikẹ́ni bá le è ka erùpẹ̀ ilẹ̀ ni yóò tó lè ka irú ọmọ rẹ.

17 Dìde, rìn òòró àti ìbú ilẹ̀ náà já, nítorí ìwọ ni Èmi yóò fi fún.”

18 Nígbà náà ni Ábúrámù kó àgọ́ rẹ̀, ó sì wá láti máa gbé lẹ́bá a igbó Mámúrè ní Hébírónì níbi tí ó tẹ́ pẹpẹ kan sí fún Olúwa.