5 Ìránṣẹ́ náà bi í wí pé, “Ǹjẹ́ bí ọmọbìnrin náà bá kọ̀ láti bá mi wá sí ilẹ̀ yìí ń kọ́? Ǹjẹ́ mo lè mú ọmọ rẹ padà lọ sí orílẹ̀-èdè níbi tí ìwọ ti wá?”
6 Ábúráhámù sì wí fún un pé, “Rí i dájú pé iwọ kò mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
7 “Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run tí ó mú mi jáde láti ilẹ̀ baba mi àti ní ilẹ̀ tí a bí mi, tí ó bá mi sọ̀rọ̀ tí ó sì búra fún mi pé, ‘Irú ọmọ rẹ ni n ó fi ilẹ̀ yìí fún’, yóò rán ańgẹ́lì rẹ̀ ṣáájú rẹ, kí ìwọ kí ó lè rí aya fẹ́ wá fún ọmọ mi láti ibẹ̀.
8 Bí obìnrin náà kò bá fẹ́ tẹ̀lé ọ wá, nígbà náà ni a tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ìbúra yìí, ṣùgbọ́n pàtàkì ni pé ìwọ kò gbọdọ̀ mú ọmọ mi padà lọ sí ibẹ̀.”
9 Ìránṣẹ́ náà sì fi ọwọ́ rẹ̀ sí abẹ́ itan Ábúráhámù olúwa rẹ̀, ó sì búra fún nítorí ọ̀rọ̀ náà.
10 Ìránṣẹ́ náà sì mú ràkunmí mẹ́wàá, pẹ̀lú onírúurú ohun dáradára láti ọ̀dọ̀ olúwa rẹ̀, ó sì dìde ó sì lọ sí Aramu-Náháráímù, sí ìlú Náhórì,
11 Ó sì mú àwọn ràkunmí náà kúnlẹ̀ nítòòsí kànga lẹ́yìn ìlú, ó ti ń di ọwọ́ ìrọ̀lẹ̀ ní àkókò tí àwọn obìnrin máa ń lọ pọn omi.