58 Wọ́n sì pe Rèbékà wọ́n sì bi í, wí pé, “Ṣe ìwọ yóò bá ọkùnrin yìí lọ.”Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, èmi yóò lọ”
59 Wọ́n sì gbà kí Rèbékà àti olùtọ́jú rẹ̀, pẹ̀lú ìránṣẹ́ Ábúráhámù àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ má a lọ.
60 Wọ́n sì súré fún Rèbékà, wọn sì wí fun un pé,“Arábìnrin wa, ìwọ yóò di ìyáẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún.Ǹjẹ́ kí àwọn irú-ọmọ rẹkí ó gba ibodè ọ̀ta a wọn.”
61 Nígbà náà ni Rèbékà àti àwọn ìránṣẹ́-bìnrin rẹ̀ múra, wọn sì gun àwọn ràkunmí, wọ́n sì bá ọkùnrin náà padà lọ. Ìránṣẹ́ náà sì mú Rèbékà ó sì bá tirẹ̀ lọ.
62 Ísáákì sì ń ti Bia-Lahai-Róì bọ, nítorí ìhà gúsù ni ó ń gbé.
63 Ísáákì sáà jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àsàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ràkunmí tí ń bọ̀ wá.
64 Rèbékà pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Ísáákì. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ràkunmí,