64 Rèbékà pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Ísáákì. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ràkunmí,
65 Ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?”Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rèbékà mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.
66 Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Ísáákì ohun gbogbo tí ó ti ṣe.
67 Nígbà náà ni Ísáákì mú Rèbékà wọ inú àgọ́ ọ ìyá rẹ̀, Ṣárà, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Ísáákì lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.