34 Lábánì sì dáhùn pé, “Mo faramọ́ ọn, ṣe bí ìwọ ti wí”
35 Ní ọjọ́ náà gan-an ni Lábánì kó gbogbo ewúrẹ̀ tí ó lámì tàbí ilà (àti akọ àti abo, tí ó ní funfun díẹ̀ lára), pẹ̀lú gbogbo àgbò dúdú, ó sì fi wọ́n sí ìtọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
36 Ibi tí Lábánì àti Jákọ́bù sì wà sí ara wọn, sì tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta. Jákọ́bù sì ń tọ́jú agbo ẹran Lábánì tí ó kù.
37 Nígbà náà ni Jákọ́bù gé ọ̀pá tẹ́ẹ́rẹ́ tútù kan lára igi pópílárì, àti álímọ́ńdì àti igi Píléénì. Ó sì bó èèpo kúrò ní ibi kọ̀ọ̀kan lára igi náà láti fún igi náà ní àwọ̀ ju ẹyọ kan lọ.
38 Ó sì mú àwọn ọ̀pá wọ̀nyí tì sí ọ̀ọ́kán agbada omi níbi tí àwọn ẹran ti lè rí i nígbà tí wọ́n bá wá mu omi
39 Tí àwọn ẹran sì ń gùn, níwájú àwọn ọ̀pá náà, wọn sì bí àwọn ẹran onílà àti alámì, àwọn tí ó ní tótòtó lára.
40 Nígbà náà ni ó ya àwọn abo ẹran kúrò nínú agbo ẹran Lábánì, ó sì yà wọ́n sọ́tọ̀ kúrò lára àgbò, ó sì mú kí wọn máa gùn pẹ̀lú àwọn àgbò Jákọ́bù dúdú nìkan, bẹ́ẹ̀ ni ó kó agbo-ẹran jọ fún ara rẹ̀ láti ara agbo ẹran Lábánì.