26 Àwọn ọmọ Dísónì ni:Hémídánì, Ésíbánì, Ítíránì àti Kéránì.
27 Àwọn ọmọ Éṣérì:Bílíhánì, Ṣááfánì, àti Ákánì.
28 Àwọn ọmọ Díṣánì ni Húsì àti Áránì.
29 Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hórì:Lótanì, Ṣóbálì, Ṣíbéónì, Áná,
30 Dísónì Éṣérì, àti Díṣánì. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Órì gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Ṣéírì.
31 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọba tí ó ti jẹ ní Édómù kí ó tó di pé a ń jẹ ọba ní Ísírẹ́lì rárá:
32 Bẹ́là ọmọ Béórì jẹ ní Édómù. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Díníhábà.