32 Bẹ́là ọmọ Béórì jẹ ní Édómù. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Díníhábà.
33 Nígbà tí Bẹ́là kú, Jóbábù ọmọ Ṣérà ti Bósírà sì jọba ní ipò rẹ̀.
34 Nígbà tí Jóbábù kú, Úṣámù láti ilẹ̀ Témánì sì jọba ní ipò rẹ̀.
35 Nígbà tí Húṣámù kú, Hádádì ọmọ Bédádì tí ó ṣẹ́gun Mídíánì ní orílẹ̀ èdè Móábù sì jọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Áfítì.
36 Lẹ́yìn ikú Ádádì, Ṣámílà tí ó wá láti Másírékà ni ó jọba lẹ́yìn rẹ̀.
37 Sámílà sì kú, Ṣáúlì ti Réhóbótì, létí odò sì jọba lẹ́yìn rẹ̀.
38 Nígbà tí Sáúlì kú, Báálì-Hánánì ọmọ Ákíbórì jọba lẹ́yìn rẹ̀.