1 Ádámù sì bá aya rẹ̀ Éfà lò pọ̀, ó sì lóyún, ó sì bí Káínì. Ó wí pé, “Pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Olúwa ni mo bí ọmọkùnrin.”
2 Lẹ́yìn náà, ó sì bí ọmọkùnrin mìíràn tí a pè ní Ábélì.Ábélì jẹ́ darandaran, Káínì sì jẹ́ àgbẹ̀.
3 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Káínì mú ọrẹ wá fún Olúwa nínú èṣo ilẹ̀ rẹ̀.
4 Ṣùgbọ́n Ábélì mú ẹran tí ó sanra wá fún Olúwa nínú àkọ́bí ẹran-ọ̀sìn rẹ̀. Olúwa sì fi ojú rere wo Ábélì àti ọrẹ rẹ̀,
5 ṣùgbọ́n Olúwa kò fi ojú rere wo Káínì àti ẹbọ rẹ̀. Nítorí náà inú bí Káínì gidigidi, ojú rẹ̀ sì fàro.