2 Nígbà náà ni màlúù méje jáde láti inú odò, wọ́n dára láti wò, wọ́n sì sanra, wọ́n sì ń jẹ koríko.
3 Lẹ́yìn àwọn wọ̀nyí, ni àwọn màlúù méje mìíràn tí kò lẹ́wà tí ó sì rù jáde wá láti inú odò Náílì, wọ́n sì dúró ti àwọn méje tí ó sanra tí ó wà ní bèbè odò náà.
4 Àwọn màlúù tí ó rù, tí kò sì lẹ́wà sì gbé àwọn tí ó lẹ́wà tí ó sanra jẹ. Nígbà náà ni Fáráò jí.
5 Ó sì tún padà sùn, ó sì lá àlá mìíràn: ó rí siírì ọkà méje tí ó kún, ó yó'mọ, ó sì dára, ó sì jáde lára igi ọkà kan ṣoṣo.
6 Lẹ́yìn wọn ni síírí ọkà méje mìíràn yọ, wọn kò yó'mọ, afẹ́fẹ́ ìlà oòrùn ti rẹ̀ ẹ́ dànù.
7 Àwọn sìírì ọkà méje tí kò yó'mọ (ọmọ rẹ̀ kò tóbi) wọ̀nyí sì gbé àwọn tí ó yó'mọ (ọmọ rẹ̀ tóbi) mì. Nígbà náà ni Fáráò jí lójú oorun, ó sì rí i pé àlá ni.
8 Ní òwúrọ̀, ọkàn rẹ̀ dàrú, nítorí náà, ó ránṣẹ́ pe gbogbo àwọn onídán àti ọ̀mọ̀ran ilẹ̀ Éjíbítì. Fáráò rọ́ àlá rẹ̀ fún wọn, ṣùgbọ́n kò rí ọ̀kan nínú wọn tí ó le sọ ìtúmọ̀ àlá náà fún un.