8 “Nítorí náà kì í ṣe ẹ̀yin ni ó rán mi wá sí ìhín bí kò ṣe Ọlọ́run. Ó fi mí ṣe baba (Olùdámọ̀ràn) fún Fáráò, alákóso fún gbogbo ilé Fáráò àti alábojútó gbogbo ilẹ̀ Éjíbítì.
9 Nísinsìn yìí, ẹ yára padà sọ́dọ̀ baba mi kí ẹ sì wí fun un pé, èyí ni ohun tí Jósẹ́fù ọmọ rẹ wí, Ọlọ́run ti fi mí ṣe àkóso fún gbogbo ilẹ̀ Éjíbítì, ẹ sọ̀kalẹ̀ wá láì jáfara.
10 Ìwọ yóò gbé ní agbégbé Gósénì, ìwọ kì yóò jìnnà sí mi-ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ-ọmọ rẹ, àwọn agbo ẹran rẹ àti agbo màlúù rẹ àti gbogbo ohun tí ìwọ ní.
11 Èmi yóò pèṣè fún yín níbẹ̀. Nítorí ó sì ku ọdún márùn ún gbáko ti ìyàn yóò fi mú. Kí ìwọ àti ilé rẹ àti ohun tí í ṣe tìrẹ má baà di aláìní.
12 “Ẹ̀yin fúnra yín àti Bẹ́ńjámínì arákùnrin mi pẹ̀lú rí i pé, lóòótọ́ lóòótọ́, èmi Jósẹ́fù ni mo ń bá a yín sọ̀rọ̀.
13 Ẹ sọ fún baba mi nípa gbogbo ọlá tí a fún mi ní ilẹ̀ Éjíbítì àti ohun gbogbo tí ẹ̀yin ti rí, kí ẹ sì mú baba mi tọ̀ mí wá sí ìhín yìí kíákíá.”
14 Nígbà náà ni ó dì mọ́ Bẹ́ńjámínì arákùnrin rẹ̀, ó sì sunkún, Bẹ́ńjámínì náà sì dì mọ́ ọn, pẹ̀lú omijé lójú.