29 Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Nóà, ó sì wí pé, “Eléyìí ni yóò tù wá nínú ni iṣẹ́ àti làálàá ọwọ́ wa, nítorí ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi gégùn-ún.”
30 Lẹ́yìn tí ó bí Nóà, Lámékì gbé fún ẹgbẹ̀ta-ó-dín-márùn-ún ọdún (595), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
31 Àpapọ̀ ọdún rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rin-ọdún-ó-dín-mẹ́talélógún (777), ó sì kú.
32 Lẹ́yìn tí Nóà pé ọmọ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún (500) ni ó bí Ṣémù, Ámù àti Jáfétì.