1 Olúwa sì wí fún Ábúrámù, “Jáde kúrò ní ile rẹ àti lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ àti kúrò ní ìdílé baba rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi ó fi hàn ọ́.
2 “Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀ èdè ńláÈmi yóò sì bùkún fún ọ.Èmi yóò sọ orúkọ rẹ di ńlá,ìbùkún ni ìwọ yóò sì jásí.
3 Àwọn tí ó súre fún ọ ni Èmi yóò súre fún,ẹnikẹ́ni tí ó bá sì fi ọ́ ré ni Èmi yóò fi ré;Nípaṣẹ̀ rẹ ni a ó sì bùkúngbogbo ènìyàn ayé”
4 Bẹ́ẹ̀ ni Ábúrámù lọ bí Olúwa ti sọ fún un. Lọ́tì náà sì bá a lọ. Ábúrámù jẹ́ ẹni àrùndínlọ́gọ́rin (75) ọdún nígbà tí ó jáde kúrò ní Háránì.