15 Gbogbo ilẹ̀ tí ìwọ ń wò o nì ní èmi ó fi fún ọ àti irú ọmọ rẹ láéláé.
16 Èmi yóò mú kí irú ọmọ rẹ kí ó pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀. Àyàfi bí ẹnikẹ́ni bá le è ka erùpẹ̀ ilẹ̀ ni yóò tó lè ka irú ọmọ rẹ.
17 Dìde, rìn òòró àti ìbú ilẹ̀ náà já, nítorí ìwọ ni Èmi yóò fi fún.”
18 Nígbà náà ni Ábúrámù kó àgọ́ rẹ̀, ó sì wá láti máa gbé lẹ́bá a igbó Mámúrè ní Hébírónì níbi tí ó tẹ́ pẹpẹ kan sí fún Olúwa.