1 Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Ábúrámù wá lójú ìran pé:Ábúrámù má ṣe bẹ̀rù,Èmi ni ààbò rẹ,Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.
2 Ṣùgbọ́n Ábúrámù wí pé, “Olúwa, alágbára, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Élíásérì ará Dámásíkù ni yóò sì jogún mi,”
3 Ábúrámù sì tún tẹ̀ṣíwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé è mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”
4 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé: “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé (ajogún) rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnrarẹ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.”