17 Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì sú, ìkòkò iná tí ń sèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrin ẹ̀là a ẹran náà.
18 Ní ọjọ́ náà gan-an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Ábúrámù, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Éjíbítì dé odò ńlá Yúfúrátè:
19 ilẹ̀ àwọn ará Kénì, Kádímónì,
20 Ítì, Pérísísì, Réfáímù.
21 Ámórì, Kénánì, Gírígásì àti Jébúsì.”