13 Ó sì fi pe Olúwa tí o bá sọ̀rọ̀ ní, “Ìwọ ni Ọlọ́run tí ó rí mi,” nítorí tí ó wí pé, “Mo ti ri ẹni tí ó rí mi báyìí.”
14 Nítorí náà ni a ṣe ń pe kànga náà ní Beeri-Lahai-Róì: kànga ẹni alààyè tí ó rí mi. Ó wà lágbedeméjì Kédásì àti Bérédì.
15 Ágárì sì bí ọmọkùnrin kan fún Ábúrámù, Ábúrámù sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ísímáélì.
16 Ábúrámù jẹ́ ẹni ọdún mẹ́rìndín-láàádọ́rùn-ún (86) nígbà tí Hágárì bí Ísímáélì fún-un.