18 Ábúráhámù sì wí fún Ọlọ́run pé, “Ṣá à jẹ́ kí Ísímáélì kí ó wà láàyè lábẹ́ ìbùkún rẹ.”
19 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo gbọ́, ṣùgbọ́n Ṣárà aya rẹ̀ yóò bí ọmọkùnrin kan fún ọ, ìwọ yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ísáákì, èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀ ní májẹ̀mú ayérayé àti àwọn irú ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
20 Ṣùgbọ́n ní ti Ísímáélì, mo gbọ́ ohun tí ìwọ wí, èmi yóò bùkún fún-un ní tòótọ́, èmi ó sì mú un bí sí i, yóò sì pọ̀ sí i, òun yóò sì jẹ́ baba fún àwọn ọmọ-ọba méjìlá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀ èdè ńlá.
21 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ìdí májẹ̀mú mi múlẹ̀ pẹ̀lú Ísáákì, ẹni tí Ṣárà yóò bí fún ọ ni ìwòyí àmọ́dún.”
22 Nígbà tí ó ti bá Ábúráhámù sọ̀rọ̀ tán, Ọlọ́run sì gòkè lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
23 Ní ọjọ́ náà gan-an ni Ábúráhámù mú Ísímáélì ọmọ rẹ̀ àti àwọn ẹrú tí a bí ní ilé rẹ̀ àti àwọn tí ó fi owó rà, ó sì kọ wọ́n ní ilà. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kọ gbogbo ọkùnrin tí ń bẹ ní ilé rẹ̀ ní ilà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa.
24 Ábúráhámù jẹ́ ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùnún (99) ọdún nígbà tí a kọ ọ́ ní ilà.