24 Ábúráhámù jẹ́ ẹni ọ̀kàndínlọ́gọ́rùnún (99) ọdún nígbà tí a kọ ọ́ ní ilà.
25 Ísímáélì ọmọ rẹ̀ jẹ́ ẹni ọdún mẹ́talá, (13).
26 Ábúráhámù pẹ̀lú rẹ̀ kọ ilà ní ọjọ́ náà gan-an.
27 Àti gbogbo ọkùnrin tí ó wà ní ilé Ábúráhámù, ìbá à ṣe èyí tí a bí ní ilé rẹ̀ tàbí èyí tí a fi owó rà lọ́wọ́ àlejò ni a kọ ní ílà pẹ̀lú rẹ̀.