1 Olúwa sì farahan Ábúráhámù ní tòsí àwọn igi ńlá Mámúrè, bí ó ti jókòó ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ rẹ̀, nígbà tí ọjọ́ kanrí tí oòrùn sì mú.
2 Ábúráhámù gbójú sókè, ó sì rí àwọn ọkùnrin mẹ́ta tí wọn dúró nítòsí rẹ̀. Nígbà tí ó rí wọn, ó sáré láti lọ pàdé wọn, ó sì tẹríba bí ó ti ń kí wọn.
3 Ó wí pé, “Bí mo bá rí ojú rere yín Olúwa mi, ẹ má ṣe lọ láì yà sọ́dọ̀ ìránṣẹ́ yín.
4 Ẹ jẹ́ kí a bu omi díẹ̀ wá kí ẹ̀yin kí ó wẹ ẹṣẹ̀ yín, kí ẹ sì sinmi lábẹ́ igi níhìn-ín.
5 Ẹ jẹ́ kí n wá oúnjẹ wá fún-un yín kí ẹ̀yin kí ó lè jẹ, kí ara sì tù yín, kí ẹ si tẹ̀ṣíwájú ní ọ̀nà yín, nígbà tí ẹ ti yà ní ọ̀dọ̀ ìránṣẹ́ yín.”Wọn sì wí pé “Ó dára.”
6 Ábúráhámù sì yára tọ Ṣárà aya rẹ̀ lọ nínú àgọ́, ó wí pé, “Tètè mú òṣùwọn ìyẹ̀fun dáradára mẹ́ta kí o sì pò ó pọ̀, kí o sì ṣe oúnjẹ.”