7 Ó sì tún sáré lọ sí ibi agbo ẹran, ó sì mú ọmọ màlúù kan fún ìránṣẹ́ rẹ̀, ìránṣẹ́ náà sì tètè ṣè é.
8 Ó sì mú wàrà àti mílíìkì àti màlúù tí ó ti pèsè, ó sì gbé e ṣíwájú wọn. Ó sì dúró nítòòsí wọn lábẹ́ igi bí wọn ti ń jẹ ẹ́.
9 Wọn bèèrè pé, “Ṣárà aya rẹ ńkọ́?”Ó dáhùn pé, “Ó wà nínú àgọ́.”
10 Nígbà náà ni Olúwa wí fún un pé, “Ṣárà aya rẹ yóò sì bí ọmọkùnrin kan.”Sárà sì ń dẹtí gbọ́ láti ẹnu ọ̀nà àgọ́ tí ó wà lẹ́yìn wọn.
11 Ábúráhámù àti Ṣárà sì ti di arúgbó: Ṣárà sì ti kọjá àsìkò ìbímọ.
12 Nítorí náà, Ṣárà rẹ́rìn-ín nínú ara rẹ̀ bí ó ti ń rò ó lọ́kàn rẹ̀ pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo ti di arúgbó tán tí olúwa mi pẹ̀lú sì ti gbó jọ̀kújọ̀kú, èmi yóò ha tún lè bímọ?”
13 Nígbà náà ni Olúwa wí fún Ábúráhámù pé, “Kín ló dé tí Ṣárà fi rẹ́rìn-ín tí ó sì wí pé, ‘Èmi yóò ha bímọ nítòótọ́, nígbà tí mo di ẹni ogbó tan?’