1 Ábúráhámù sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kádésì àti Ṣúrì; ó sì gbé ní ìlú Gérárì fún ìgbà díẹ̀.
2 Ábúráhámù sì sọ ní ti Ṣárà aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Ábímélékì ọba Gérárì sì ránṣẹ́ mú Ṣárà wá sí ààfin rẹ̀.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Ábímélékì wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀, aya aláya ni.”
4 Ṣùgbọ́n Ábímélékì kò tí ì bá obìnrin náà lò pọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀ èdè aláìlẹ́bi bí?