17 dájúdájú, Èmi yóò bùkún ọ, Èmi yóò sì mú kí ìran rẹ yìí kí ó pọ̀ bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí i yanrìn etí òkun. Irú ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀ta wọn,
18 àti nípaṣẹ̀ irú ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀ èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́ràn sí mi lẹ̀nu”
19 Nígbà náà ni Ábúráhámù padà tọ àwọn ìrànṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Báá-Ṣébà Ábúráhámù sì dúró ní Báá-Ṣébà.
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Ábúráhámù pé, “Mílíkà aya Náhórì bí àwọn ọmọkùnrin fún-un.
21 Úsì, àkọ́bí rẹ̀, Búsì arákùnri rẹ̀, Kémúélì (Baba Árámù).
22 Kéṣédì, Áṣọ̀, Pílídásì, Jídíláfù, àti Bétúélì.”
23 Bétúélì sì ni baba Rèbékà. Mílíkà sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Náhórì arákùnrin Ábúráhámù.