21 Wí pé, “Ìwa àwọn ọkùnrin wọ̀nyí dára, ẹ jẹ́ kí wọn máa gbé ní àárin wa, kí wọn sì máa ṣòwò, ilẹ̀ kúkú wà rẹpẹtẹ tó gbààyè dáradára. A lè fẹ́ àwọn ọmọ wọ̀n, ki wọn sì fẹ́ tiwa pẹ̀lú.
22 Ṣùgbọ́n kin ní kan ni a lè ṣe kí wọn tó gbà láti gbé pẹ̀lú wa, ìyẹn sì ni pé àwọn ọkùnrin wa yóò kọlà bí i tiwọn
23 Ṣe bí àwọn ẹran wọn àti ẹrú wọn àti àwọn ohun ọ̀sìn wọn ni yóò di tiwa bí a bá lè gbà bẹ́ẹ̀, wọn yóò sì máa gbé ni àárin wa.”
24 Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ń jáde lẹ́nu bodè ìlú náà sì gbọ́ ti Ámórì àti Ṣékémù ọmọ rẹ̀. Gbogbo ọkùnrin ìlú náà sì kọlà.
25 Lẹ́yìn ọjọ́ kẹ́ta, nígbà tí gbogbo wọn sì wà nínú ìrora. Àwọn ọmọ Jákọ́bù méjì, Símónì àti Léfì tí ó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Dínà, sì mú idà wọn pẹ̀lú ìgboyà, wọ́n sì pa gbogbo ọkùnrin ìlú náà.
26 Wọ́n pa Ámórì àti Ṣékémù ọmọ rẹ̀, wọ́n mú Dínà kúrò ní ilé wọn, wọ́n sì jáde.
27 Àwọn ọmọ Jákọ́bù sì wọlé àwọn tí a pa, wọ́n sì kó ẹrù ìlú tí a ti ba ògo arábìnrin wọn jẹ́.