35 Nígbà tí Húṣámù kú, Hádádì ọmọ Bédádì tí ó ṣẹ́gun Mídíánì ní orílẹ̀ èdè Móábù sì jọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Áfítì.
36 Lẹ́yìn ikú Ádádì, Ṣámílà tí ó wá láti Másírékà ni ó jọba lẹ́yìn rẹ̀.
37 Sámílà sì kú, Ṣáúlì ti Réhóbótì, létí odò sì jọba lẹ́yìn rẹ̀.
38 Nígbà tí Sáúlì kú, Báálì-Hánánì ọmọ Ákíbórì jọba lẹ́yìn rẹ̀.
39 Nígbà tí Baali-Hánánì ọmọ Ákíbórì kú, Ádádì ni ó jọba lẹ́yìn rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Páù, Méhétà-bélì ọmọbìnrin Mátírédì àti ọmọ-ọmọ Mé-ṣáhábù ni ìyàwó rẹ̀.
40 Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ìjòyè tí ó ti ọ̀dọ̀ Ísọ̀ jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí:Tínínà, Álífánì, Jététì.
41 Ohólíbámà, Élà, Pínónì,