33 Ó sì dá a mọ̀, ó wí pé, “Áà! aṣọ ọmọ mi ni, ẹranko búburú ti pa á jẹ, láìṣe àníàní, ó ti fa Jósẹ́fù ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.”
34 Nígbà náà ni Jákọ́bù fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, ó sì sọ̀fọ̀ ọmọ rẹ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́
35 Gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́kùnrin, lóbìnrin wá láti tù ú nínú, ṣùgbọ́n kò gbà. Ó wí pé, “Rárá, nínú ọ̀fọ̀ yìí ni èmi yóò lọ sí iṣà òkú lọ́dọ̀ ọmọ mi.” Baba Jósẹ́fù sì sunkún fún un.
36 Ní gbogbo àkókò wọ̀nyí, àwọn ará Mídíánì ta Jósẹ́fù ní Éjíbítì fún Pótífà, ọ̀kan nínú àwọn ìjòyè Fáráò, tí í ṣe olórí ẹ̀sọ́.