20 Ọjọ́ kẹ́ta sì jẹ́ ọjọ́ ìbí Fáráò, ó sì ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìjòyè e rẹ̀. Ó sì mú olórí agbọ́tí àti olórí aláṣè jáde kúrò nínú ẹ̀wọ̀n.
21 Ó dá olórí agbọ́tí padà sí ipò tí ó wà tẹ́lẹ̀, kí ó ba à le máa ṣe iṣẹ́ rẹ̀ bí i ti àtẹ̀yìnwa,
22 Ṣùgbọ́n, ó so olórí alásè kọ́ sórí igi, gẹ́gẹ́ bí Jósẹ́fù ti sọ fún wọn nínú ìtúmọ̀ rẹ̀ sí àlá wọn.
23 Ṣùgbọ́n, olórí agbọ́tí kò rántí Jósẹ́fù mọ́, kò tilẹ̀ ronú nípa rẹ̀.