28 “Bí mo ti wí fún Fáráò ní ìṣáájú náà ni: Ọlọ́run fi ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ han Fáráò.
29 Ọdún méje tí oúnjẹ yóò pọ yanturu ń bọ̀ wà ní Éjíbítì.
30 Ṣùgbọ́n ọdún méje mìíràn tí ìyàn yóò mú yóò tẹ̀lé e, nígbà náà ni a ó tilẹ̀ gbàgbé pé ọdún méje tí ọ̀pọ̀ oúnjẹ wà yanturu tilẹ̀ ti wà rí, ìyàn yóò sì run gbogbo ilẹ̀ náà,
31 A kò ní rántí àsìkò ọ̀pọ̀ oúnjẹ yanturu náà mọ́ nítorí pé ìyàn tí yóò tẹ̀lé e yóò pọ̀ púpọ̀.
32 Ìdí tí Ọlọ́run fi fi àlá náà han fún Fáráò ní ọ̀nà méjì ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni pé, Ọlọ́run ti pinnu pé yóò sẹlẹ̀ bẹ́ẹ̀ dandan, àti pé kò ni pẹ́ tí Ọlọ́run yóò fi ṣe é.
33 “Ìmọ̀ràn mi ni wí pé, jẹ́ kí Fáráò wá ọlọgbọ́n ènìyàn kan ní ilẹ̀ Éjíbítì, kí ó sì fi ṣe alákòóṣo iṣẹ́ àgbẹ̀ ilẹ̀ Éjíbítì.
34 Kí Fáráò sì yan àwọn alábojútó láti máa gba idá márùn-ún ìkórè oko ilẹ̀ Éjíbítì ní àsìkò ọdún méje ọ̀pọ̀.