31 Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti bọ́jú tan, ó jáde wá, ó ṣe ọkàn ọkùnrin, ó sì wí fún wọn pé, kí wọ́n gbé oúnjẹ wá kí wọ́n le è jẹun.
32 Wọ́n gbé oúnjẹ tirẹ̀ fun-un lọ́tọ̀, àti fún àwọn ará Éjíbítì tí ó wá ba jẹun náà lọ́tọ̀, nítorí ará Éjíbítì kò le bá ará Ébérù jẹun nítorí ìríra pátapáta ló jẹ́ fún àwọn Éjíbítì.
33 A mú àwọn ọkùnrin náà jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bí wọ́n ṣe dàgbà sí, láti orí ẹ̀gbọ́n pátapáta dé orí èyí tí ó kéré pátapáta, wọ́n sì ń wo ara wọn tìyanu tìyanu.
34 A sì bu oúnjẹ fún wọn láti orí tábìlì Jósẹ́fù. Oúnjẹ Bẹ́ńjámínì sì tó ìlọ́po márùn-ùn ti àwọn tókù. Wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu lọ́dọ̀ rẹ̀ láì sí ìdíwọ́.