25 Báyìí ni wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Éjíbítì wá sí ọ̀dọ̀ Jákọ́bù baba wọn ní ilẹ̀ Kénánì.
26 Wọn wí fún un pé, “Jósẹ́fù sì wà láàyè! Kódà òun ni alákòóṣo ilẹ̀ Éjíbítì” Ẹnu ya Jákọ́bù, kò sì gbà wọ́n gbọ́
27 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n sọ ohun gbogbo tí Jósẹ́fù ti sọ fún wọn fún un tí ó sì rí kẹ̀kẹ́ ẹrù tí Jósẹ́fù fi ránṣẹ́ láti gbé e padà wá, iyè Jákọ́bù, baba wọn ṣọ.
28 Ísírẹ́lì sì wí pé, “Mo gbà dájúdájú wí pé, Jósẹ́fù ọmọ mi wà láàyè. Èmi ó lọ rí i kí n tó kú.”