13 “Ṣébúlúnì yóò máa gbé ní etí òkun,yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi,agbégbé rẹ yóò tàn ká títí dé Ṣídónì.
14 “Ísákárì jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbáratí ó sùn sílẹ̀ láàrin àpò ẹrù méjì.
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó,àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó,yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà,yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
16 “Dánì yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì.
17 Dánì yóò jẹ́ ejo ni pópónààti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà,tí ó bu ẹsin jẹ ní ẹṣẹ̀,kí ẹni tí n gùn-un bá à le è subú sẹ́yìn.
18 “Mo ń dúró de ìtúsilẹ̀ rẹ, Olúwa
19 “Ẹgbẹ́-ogun àwọn ẹlẹ́sin yóò kọ lu Gádì,ṣùgbọ́n yóò kọ lu wọ́n ní gìgíṣẹ̀ wọn.