20 “Oúnjẹ Áṣérì yóò dára;yóò ṣe àṣè tí ó yẹ fún ọba.
21 “Náfútalì yóò jẹ́ abo àgbọ̀nríntí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ daradara.
22 “Jóṣẹ́fù jẹ́ àjàrà eléṣo,àjàrà eléṣo ní etí odò,tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
23 Pẹ̀lú ìkorò,àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́,wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra,
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára,ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le,nítorí ọwọ́ alágbára Jákọ́bù,nítorí olútọ́jú àti aláàbò àpáta Ísírẹ́lì.
25 Nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́,nítorí Olódùmarè tí ó bù kún ọ,pẹ̀lú láti ọ̀run wá,ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìṣàlẹ̀,ìbùkún ti ọmú àti ti inú,
26 ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì,ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé.Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Jóṣẹ́fù,lé ìpéǹpéjú ọmọ aládé láàrin arákùnrin rẹ̀.