8 “Júdà, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ,ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀ta rẹ,àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Júdà,o darí láti ìgbẹ́ ọdẹ, ọmọ mi.Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún,Ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Júdàbẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìsàkóso kì yóò kúròláàrin ẹṣẹ̀ rẹ̀, títí tí ẹni tí ó ni í yóò fi dé,tí gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè yóò máa wárí fún un.
11 Yóò má ṣo ọmọ ẹsin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà àtiọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù.Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wùrẹ̀ nù nínú omi-pupa ti eṣo àjàrà (gíréèpù).
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ,ẹyín rẹ yóò sì funfunu pẹ̀lú omi-ọyàn
13 “Ṣébúlúnì yóò máa gbé ní etí òkun,yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi,agbégbé rẹ yóò tàn ká títí dé Ṣídónì.
14 “Ísákárì jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbáratí ó sùn sílẹ̀ láàrin àpò ẹrù méjì.