1 Èyí ni àkọsílẹ̀ ìran Ádámù.Nígbà tí Ọlọ́run dá ènìyàn, ó dá a ní àwòrán Ọlọ́run.
2 Ó dá wọn ní akọ àti abo, ó sì súre fún wọn. Nígbà tí ó dá wọn tan ó pè wọ́n ní “ènìyàn.”
3 Nígbà tí Ádámù di ẹni Àádóje ọdún (130), ó bí ọmọkùnrin kan tí ó jọ ọ́, tí ó jẹ́ àwòrán ara rẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Ṣétì.
4 Lẹ́yìn ìgbà tí ó bí Ṣétì, ó tún wà láàyè fún ẹgbẹ̀rin ọdún (800), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
5 Àpapọ̀ ọdún tí Ádámù gbé ní orí ilẹ̀ jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún-ọdún-ó-lé-ọgbọ̀n (930), ó sì kú.