20 Ó sì yára da omi inú ìkòkò omi rẹ̀ sínú ìbùmu, ó sáré padà lọ síbi omi láti pọn sí i wá fún àwọn ràkunmí, títí tí ó fi pọn fún gbogbo wọn.
21 Láì sọ ọ̀rọ̀ kan, ìránṣẹ́ yìí ń wo ọmọbìnrin náà fínnífínní láti mọ̀ bóyá Ọlọ́run ti ṣe ìrìn-àjò òun ní rere tàbí bẹ́ẹ̀ kọ́.
22 Lẹ́yìn tí àwọn ràkunmí náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọn sékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n sékélì wúrà mẹ́wàá.
23 Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
24 Ó dáhùn pé, “Bétúélì ọmọ tí Mílíkà bí fún Náhórì ni baba mi”
25 Ó sì fi kún un pé, “A ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ koríko àti oúnjẹ fún àwọn ràkunmí yín àti yàrá pẹ̀lú fún-un yín láti wọ̀ sí.”
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa.