22 Lẹ́yìn tí àwọn ràkunmí náà ti mu omi tán, ni ọkùnrin náà mú òrùka wúrà ààbọ̀ ìwọn sékélì àti júfù méjì fún ọwọ́ rẹ̀, tí ìwọ̀n sékélì wúrà mẹ́wàá.
23 Lẹ́yìn náà, ó béèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ í ṣe? Jọ̀wọ́ wí fún mi, ǹjẹ́ ààyè wà ní ilé baba rẹ láti wọ̀ sí ní alẹ́ yìí?”
24 Ó dáhùn pé, “Bétúélì ọmọ tí Mílíkà bí fún Náhórì ni baba mi”
25 Ó sì fi kún un pé, “A ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ koríko àti oúnjẹ fún àwọn ràkunmí yín àti yàrá pẹ̀lú fún-un yín láti wọ̀ sí.”
26 Nígbà náà ni ọkùnrin náà tẹríba, ó sì sin Olúwa.
27 Wí pe, “Ògo ni fún Olúwa, Ọlọ́run Ábúráhámù olúwa mi ti kò jẹ́ kí àánú àti òtítọ́ rẹ̀ kí ó yẹ̀ lọ́dọ̀ olúwa mi. Ní ti èmi Olúwa ti darí ìrìn-àjò mi sí ilé ìbátan olúwa mi.”
28 Ọmọbìnrin náà sì sáré, ó sì lọ sọ ohun gbogbo wọ̀nyí fún àwọn ará ilé ìyá rẹ̀.