Jẹ́nẹ́sísì 24:44-50 BMY

44 tí ó bá sì wí fún mi pé, “Mu ún, èmi yóò sì tún pọn omi fún àwọn ràkunmí rẹ pẹ̀lú,” Jẹ́ kí ẹni náà jẹ́ ẹni tí Olúwa yàn fún ọmọ Ábúráhámù, olúwa mi.’

45 “Kí n sì tó gbàdúrà tán nínú ọkàn mi, Rèbékà jáde wá pẹ̀lú ìkòkò omi rẹ̀ ní èjìká rẹ̀, ó sì lọ sí ibi ìsun omi ó sì pọn omi. Mo sì wí fun un pé, ‘Jọ̀wọ́ fún mi ni omi mu.’

46 “Kíákíá ni ó sọ ìkòkò rẹ̀ kalẹ̀ láti èjìká rẹ̀, ó sì wí fún mi pé, ‘Mu ún, èmi yóò sì tún fún àwọn ràkúnmí rẹ mu pẹ̀lú.’ Mo sì mu, ó sì tún fún àwọn ràkúnmí mi mu pẹ̀lú.

47 “Mo béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, ‘ọmọ ta ní ìwọ í ṣe?’“Ó sì wí fún mi pé, ‘ọmọbìnrin Bétúélì tí í ṣe ọmọ Náhórì ni òun, Mílíkà sì ni ìyá òun.’“Nígbà náà ni mo fi òrùka náà bọ imú rẹ̀, mo sì fi ẹ̀gbà-ọwọ́ náà si ní ọwọ́.

48 Mo sì wólẹ̀ mo sì sin Olúwa, Ọlọ́run Ábúráhámù olúwa à mi, ẹni tí ó ṣe amọ̀nà mi láti rí ọmọ ọmọ arákùnrin olúwa mi, mú wá fún ọmọ rẹ̀ (Ísáákì).

49 Ǹjẹ́ nísin yìí bí ẹ̀yin yóò bá fi inú rere àti òtítọ́ bá olúwa mi lò, ẹ sọ fún mi, bí bẹ́ẹ̀ sì kọ́, ẹ sọ fún mi, kí ó le è mọ ọ̀nà tí èmi yóò yà sí.”

50 Lábánì àti Bétúélì sì dáhùn pé, “Lọ́dọ̀ Olúwa ni èyi ti wá, nítorí náà àwa kò le sọ rere tàbí búburú fún ọ.