31 Jákọ́bù dáhùn pé, “Kò burú, ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ta ogún ìbí rẹ fún mi ná.”
32 Éṣáù sì dáhùn pé, “Wò ó mo ti fẹ́rẹ̀ẹ́ kú, àǹfààní kín sì ni ogún ìbí jẹ́ fún mi?”
33 Ṣùgbọ́n, Jákọ́bù dáhùn pé, “Kọ́kọ́ búra fún mi pé tèmi ni ogún ìbí náà yóò jẹ́.” Báyìí ni Ísọ̀ búra tí ó sì gbé ogún ìbí rẹ̀ tà fún Jákọ́bù.
34 Nígbà náà ni Jákọ́bù fún Ísọ̀ ní oúnjẹ àti ọbẹ̀. Ó jẹ ẹ́, ó sì jáde lọ.Báyìí ni Ísọ̀ ṣe aláìka ogún ìbí rẹ̀ sí.